ABO OLORUN DAJU
Awon ota yi Dafidi po won si fe lati baa ja tabi see ni jamba, sugbon kii se eni ti ko ni abo. O ni Olorun ti o je alabo re, nitori naa o kepe Olorun o wipe ‘Sugbon emi gbekele o, Oluwa, emi ni, iwo ni Olorun mi, igba mi nbe ni owo re, gba mi ni owo awon ota mi, ati ni owo awon tin se inunibini si mi. Se oju re ki o mole si iranse re lara, gba mi nitori anu re, mase je ki oju ko ti mi Oluwa, nitori ti emi nke pe o, eniyan buburu ni ki oju ki o ti, awon ni ki a mu dake ni isa-oku.
(Orin Dafidi 31:14-17)
EKO
Awon kristieni ni eto lati beere lowo Olorun fun ibukun ati abo, niwon bi a ti je omo Olorun, a ni anfani lati beere ohunkohun ti a ba nfe. Ibere wa ko ye ki o duro lori ohun ti ara, o ye ki a beere fun abo, bakan naa nigba ti kristieni ba ti gbadura a ni lati gbagbo pelu ireti. Olorun ti o feran awon omo re ko ni dakun lati bukun won, yi o si bi awon ota wa subu labe ese wa.
ADURA
Olorun olufe, mo mo wipe emi ni olori-ire julo ni gbogbo agbaye nitori pe mo ni o ni Olorun, mo si fi igbekele mi ninu re mule. Mo pase ki gbogbo ipenija aye ti o yimika ki o teri ba ni oruko Jesu Kristi, niwon igba ti mo je omo Olorun, mo ni ase unla, mo pase ki ohun gbogbo teti simi, mo fi Satani bu, ki ohun inilara gbogbo ki o baje ni oruko Jesu Kristi. Amin.
